1Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo;
2Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa;
3Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi;
4Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn;
5Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn;
6Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀;
7Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká
8Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára;
9Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́,
10Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n;
11Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi;
12Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀;
13Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi
14Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere;
15Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo;
16Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú;
17Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́,
18Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn;
19Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀,
20Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́;
21Ibi ni ó mú ikú ìkà wá,
22Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà;