1Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí;
2Di asà àti àpáta mú,
3Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ
4Kí wọn kí ó dààmú,
5Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́,
6Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́,
7Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi,
8Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì.
9Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú Olúwa,
10Gbogbo egungun mi yóò wí pé,
11Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde;
12Wọ́n fi búburú san ìre fún mi;
13Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀;
14èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀
15Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ;
16Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ
17Yóò ti pẹ́ tó Olúwa, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ?
18Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá;
19Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi
20Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà,
21Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà!
22Ìwọ́ ti rí i Olúwa; má ṣe dákẹ́!
23Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi,
24Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ,
25Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!”
26Kí ojú kí ó tì wọ́n,
27Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi
28Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ,