1Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo;
2Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù;
3Ẹ kọ orin tuntun sí i;
4Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin,
5Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́;
6Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run,
7Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò;
8Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa:
9Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀;
10Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán;
11Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé,
12Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀,
13Olúwa wò láti ọ̀run wá;
14Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́
15ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà,
16A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun;
17Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun;
18Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀,
19Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú
20Ọkàn wa dúró de Olúwa;
21Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀,
22Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa,