1Olúwa,
2Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ;
3Ẹni tí ó dúró tì ọ́
4Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa,
5ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi,
6Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá,
7Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi
8Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa:
9Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára,
10Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin,
11Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa,
12Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa?
13Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà,
14Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀;
15Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa,
16Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi;
17Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi;
18Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi,
19Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi,
20Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀;
21Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́;
22Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run,