1Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́,
2Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè
3Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun
4Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,”
5Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè,
6Ní ojú fèrèsé ilé è mi
7Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan
8Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà,
9Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀,
10Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀,
11(Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí,
12bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún
13Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu
14“Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé;
15Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ;
16Mo ti tẹ́ ibùsùn mi
17Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi
18Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀;
19Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé;
20Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́
21Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà;
22Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà,
23Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀,
24Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi
25Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀,
26Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀.
27Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú,