1Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ,
2bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ,
3Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ
4Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́,
5Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ,
6Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ;
7Kò ní olùdarí,
8síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò
9Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ?
10Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,
11Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà
12Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú,
13tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò,
14tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀
15Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn;
16Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra,
17Ojú ìgbéraga,
18ọkàn tí ń pète ohun búburú,
19ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu
20Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́
21Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé
22Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ;
23Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà,
24Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú,
25Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ
26Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan,
27Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan
28Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná?
29Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya;
30Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè
31Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje
32Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú;
33Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀,
34Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè,
35Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn;