1Ǹjẹ́ ọgbọ́n kò ha ń kígbe síta?
2Ní ibi gíga ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà,
3ní ẹgbẹ́ ibodè tí ó wọ ìlú,
4“Sí i yín ẹ̀yin ènìyàn, ní mo ń kígbe pè;
5Ẹ̀yin aláìmọ̀kan, ẹ kọ́gbọ́n;
6Ẹ gbọ́, nítorí tí èmi ó sọ̀rọ̀ ohun iyebíye;
7ẹnu mi ń sọ ohun tí í ṣe òtítọ́,
8Gbogbo ọ̀rọ̀ ẹnu mi ni ó tọ́,
9Fún olóye gbogbo rẹ̀ ni ó tọ̀nà;
10Yan ẹ̀kọ́ mi dípò fàdákà,
11nítorí ọgbọ́n ṣe iyebíye jù iyùn lọ,
12“Èmi, ọgbọ́n ń gbé pẹ̀lú òye;
13Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìkórìíra ibi
14Ìmọ̀ràn àti ọgbọ́n tí ó yè kooro jẹ́ tèmi
15Nípasẹ̀ mi ni ọba ń ṣàkóso
16Nípasẹ̀ mi àwọn ọmọ-aládé ń ṣàkóso,
17Mo fẹ́ràn àwọn tí ó fẹ́ràn mi,
18Lọ́dọ̀ mi ni ọrọ̀ àti ọlá wà,
19Èso mi dára ju wúrà dáradára lọ;
20Mò ń rìn ní ọ̀nà òdodo,
21mò ń fi ọrọ̀ fún gbogbo àwọn tí ó fẹ́ràn mi
22“Èmi ni Olúwa kọ́kọ́ dá nínú iṣẹ́ rẹ̀.
23a ti yàn mí láti ayérayé,
24Nígbà tí kò tí ì sí Òkun, ni a ti bí mi,
25kí a tó fi àwọn òkè sí ipò wọn,
26kí ó tó dá ilẹ̀ ayé tàbí àwọn oko rẹ̀
27Mo wà níbẹ̀ nígbà tí ó fi àwọn ọ̀run sí ipò wọn,
28nígbà tí ó ṣẹ̀dá òfúrufú lókè
29nígbà tí ó ṣe ààlà fún omi Òkun
30Nígbà náà èmi ni gbẹ́nàgbẹ́nà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀
31Mo ń yọ̀ nínú gbogbo àgbáyé tí ó dá
32“Nítorí náà báyìí, ẹ̀yin ọmọ mi,
33Fetí sí ìtọ́sọ́nà mi kí o sì gbọ́n;
34Ìbùkún ni fún ẹni tí ó fetísílẹ̀ sí mi,
35Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá rí mi rí ìyè
36Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti rí ń pa ara rẹ̀ lára