1Olúwa, Ọlọ́run tí ó gbà mí là,
2Jẹ́ kí àdúrà mi kí ó wá sí iwájú rẹ;
3Nítorí ọkàn mi kún fún ìpọ́njú
4A kà mí mọ́ àwọn tí wọ́n lọ sí ọ̀gbun ilẹ̀
5A yà mí sọ́tọ̀ pẹ̀lú àwọn òkú
6Ìwọ tí ó fi mí sí kòtò jíjìn,
7Ìbínú rẹ ṣubú lé mi gidigidi;
8Ìwọ tí gba ọ̀rẹ́ mi tí ó súnmọ́ mi kúrò lọ́wọ́ mi
9ojú mi káàánú nítorí ìpọ́njú.
10Ìwọ ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ hàn fún òkú bi?
11A ó ha fi ìṣeun ìfẹ́ rẹ hàn ní ibojì bí,
12A ha lè mọ iṣẹ́ ìyanu rẹ ní òkùnkùn bí
13Ṣùgbọ́n mo kígbe sí ọ fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa;
14Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí
15Láti ìgbà èwe mi, ìṣẹ́ ń ṣẹ́ mi,
16Ìbínú rẹ ti kọjá lára mi;
17Ní gbogbo ọjọ́ ni wọn yí mi ká bí ìkún omi;
18Ìwọ ti mú ọ̀rẹ́ àti olùfẹ́ mi kúrò lọ́dọ̀ mi;