1Ọlọ́run, má ṣe dákẹ́;
2Wo bí àwọn ọ̀tá rẹ ti ń rọ́kẹ̀kẹ̀ lọ,
3Pẹ̀lú àrékérekè ni wọn dìtẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ;
4Wọn wí pé, “wá, ẹ jẹ́ kí á pa wọ́n run bí orílẹ̀-èdè,
5Wọ́n gbìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú ọkàn kan;
6Àgọ́ Edomu àti ti àwọn ará Iṣmaeli,
7Gebali, Ammoni àti Amaleki,
8Asiria pẹ̀lú ti darapọ̀ mọ́ wọn
9Ṣe sí wọn bí ìwọ ti ṣe sí Midiani
10ẹni tí ó ṣègbé ní Endori
11Ṣe àwọn ọlọ́lá wọn bí Orebu àti Seebu,
12tí ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a gbà ní ìní
13Ìwọ Ọlọ́run, ṣe wọ́n bí ààjà,
14Bí iná ti í jó igbó,
15bẹ́ẹ̀ ni kí o fi ẹ̀fúùfù líle rẹ lépa wọn
16Fi ìtìjú kún ojú wọn,
17Jẹ́ kí ojú kí ó tì wọ́n, kí wọ́n sì dààmú láéláé
18jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ìwọ, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa: