1Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa
2Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wá,
3Ẹ fún ìpè ní oṣù tuntun
4Èyí ni àṣẹ fún Israẹli,
5Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Josẹfu
6Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúrò ní èjìká yín,
7Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là,
8“Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín,
9Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrín yín;
10Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,
11“Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi;
12Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn
13“Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi
14ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn
15Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀.
16Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín