1Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi;
2Èmi ó la ẹnu mi ní òwe,
3ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀,
4Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́
5Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu
6nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n
7Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run
8Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn,
9Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun,
10Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́
11Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe,
12Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
13Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá
14Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn
15Ó sán àpáta ní aginjù
16Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta
17Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i
18Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò
19Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé
20Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde,
21Nígbà tí Olúwa gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi;
22nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́,
23Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
24Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ,
25Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli;
26Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá
27Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀,
28Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn,
29Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ
30Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún,
31ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn
32Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú;
33O fi òpin sí ayé wọn nínú asán
34Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n,
35Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn;
36Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n
37ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i,
38Síbẹ̀ ó ṣàánú;
39Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n,
40Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù
41Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò;
42Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀:
43ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti,
44Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀;
45Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run,
46Ó fi ọkà wọn fún láńtata,
47Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́
48Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín,
49Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára,
50Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀,
51Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti,
52Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran;
53Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n
54Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀
55Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn
56Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò
57Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà,
58Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn;
59Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn,
60Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀,
61Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn,
62Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́,
63Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn,
64àfi àlùfáà wọn fún idà,
65Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun,
66Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà;
67Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu,
68ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda,
69Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga,
70Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀
71Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn
72Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn;