1Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
2Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀;
3Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ!
4Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ;
5Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe,
6Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ,
7Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀,
8Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn,
9Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa,
10Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò;
11Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n
12Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí
13Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,
14ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ
15Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ,
16Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run;
17Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i,
18Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi,
19ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́
20Ìyìn ni fún Ọlọ́run