1Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ,
2Nítorí tí ọfà rẹ kàn mọ́ mi ṣinṣin,
3Kò sí ibi yíyè ní ara à mi, nítorí ìbínú rẹ;
4Nítorí àìṣedéédéé mi ti borí mi mọ́lẹ̀;
5Ọgbẹ́ mi ń rùn ó sì díbàjẹ́
6Èmi ń jòwèrè, orí mi tẹ̀ ba gidigidi
7Nítorí ẹ̀gbẹ́ mi kún fún ìgbóná tí ń jóni
8Ara mi hù, a sì wó mi jẹ́gẹjẹ̀gẹ;
9Olúwa, gbogbo ìfẹ́ mi ń bẹ níwájú rẹ;
10Àyà mi ń mí hẹlẹ, agbára mi yẹ̀ mí sílẹ̀;
11Àwọn ọ̀rẹ́ mi àti àwọn ẹlẹgbẹ́ mi dúró lókèèrè réré kúrò níbi ìpọ́njú mi,
12Àwọn tí n wá ẹ̀mí mi dẹ okùn sílẹ̀ fún mi;
13Ṣùgbọ́n mo dàbí adití odi, èmi kò gbọ́ ọ̀rọ̀;
14Nítòótọ́, mo rí bí ọkùnrin tí kò gbọ́rọ̀,
15Ṣùgbọ́n sí ọ Olúwa, ìwọ ni mo dúró dè;
16Nítorí tí mo gbàdúrà, “Gbóhùn mi, kí wọn má ba à yọ̀ mí;
17Nítorí tí mo ti ṣetán láti ṣubú,
18Mo jẹ́wọ́ ìrékọjá mi;
19Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí pàtàkì, wọ́n lágbára púpọ̀,
20Àwọn tí wọn ń fi ibi san rere fún mi
21Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, ìwọ Olúwa!
22Yára láti ràn mí lọ́wọ́,