1Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;
2Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:
3Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,
4Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;
5Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;
6Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;
7Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;
8Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;
9Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;
10Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;
11Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;
12Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;
13Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;
14Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀
15Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;
16Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já
17Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;
18Ó sì pa àwọn ọba olókìkí
19Sihoni, ọba àwọn ará Amori
20Àti Ogu, ọba Baṣani;
21Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
22Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,
23Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;
24Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;
25Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo
26Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;