1Ẹ yin Olúwa.
2Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa,
3Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun;
4Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀;
5Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi,
6Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú,
7Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá:
8Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti,
9Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti,
10Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀,
11Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu,
12Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
13Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé;
14Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀,
15Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà,
16Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀;
17Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀;
18Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn:
19Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa,
20Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa;
21Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá,