1Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún
2Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa,
3Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́?
4Rántí mi, Olúwa,
5kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn,
6Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe,
7Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti,
8Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ
9O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ;
10O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn,
11Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn;
12Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́
13Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe
14Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́,
15Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún
16Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose
17Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì
18Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀;
19Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù
20Wọ́n pa ògo wọn dà
21Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n
22iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu
23Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run
24Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà
25Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn
26Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè
27láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè
28Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori,
29wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe
30Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i,
31A sì ka èyí sí òdodo fún un àti
32Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú,
33Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run.
34Wọn kò pa àwọn ènìyàn run
35Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè,
36Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn
37Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ
38Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,
39Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́,
40Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀
41Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́,
42Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú
43Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n,
44Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro
45ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn
46Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn
47Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa,
48Olùbùkún ni Olúwa,