1Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.
2Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ;
3ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ.
4Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ,
5O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀;
6Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ;
7Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ,
8wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè,
9Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀;
10Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn àfonífojì;
11Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi
12Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi
13Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá;
14Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ
15Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀,
16Àwọn igi Olúwa ni a bu omi rin dáradára,
17Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn
18Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó;
19Òṣùpá jẹ́ àmì fún àkókò
20Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru,
21Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn
22Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ,
23Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,
24Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa!
25Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú,
26Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn,
27Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́
28Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn,
29Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́
30Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ,
31Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé;
32ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì,
33Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí Olúwa:
34Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn
35Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé