1Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ,
2Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀:
3Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀,
4Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
5Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà:
6Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀:
7Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú,
8Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán:
9Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún;
10Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde;
11Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà,
12Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́,
13Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde!
14Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni;
15Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí;
16Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀,
17Dẹtí rẹ sílẹ̀,
18Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ;
19Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa,
20Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára
21kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́;
22Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà:
23nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn,
24Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́;
25Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
26Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́,
27Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san,
28Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì,
29Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀?