1Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa;
2Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò,
3Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba,
4A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu;
5Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa;
6Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria
7Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́,
8Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa,
9Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa
10Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò,
11Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni,
12Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn;
13Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta;
14Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú;
15Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa;
16Adé ti ṣí kúrò ní orí wa
17Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa,
18Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro
19Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé;
20Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà?
21Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà;
22àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá