1Jobu sì dáhùn ó sì wí pé,
2“Èmi mọ̀ pe bẹ́ẹ̀ ni ní òtítọ́.
3Bí ó bá ṣe pé yóò bá a jà,
4Ọlọ́gbọ́n nínú àwọn alágbára ní ipa ní Òun.
5Ẹni tí ó sí òkè nídìí tí wọn kò sì mọ́:
6Tí ó mi ilẹ̀ ayé tìtì kúrò ní ipò rẹ̀,
7Ó pàṣẹ fún oòrùn kò sì le è ràn,
8Òun nìkan ṣoṣo ni ó ta ojú ọ̀run,
9Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Beari àti Orioni,
10Ẹni tí ń ṣe ohun tí ó tóbi jù àwárí lọ,
11Kíyèsi i, ó ń kọjá lọ ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ mi, èmi kò sì rí i,
12Kíyèsi i, ó já a gbà lọ, ta ni ó lè fà á padà?
13Ọlọ́run kò ní fa ìbínú rẹ̀ sẹ́yìn,
14“Kí ní ṣe tí èmi ti n o fi ba ṣàròyé?
15Bí ó tilẹ̀ ṣe pé mo ṣe aláìlẹ́bi, èmi kò gbọdọ̀ dá a lóhùn;
16Bí èmi bá sì ké pè é, tí Òun sì dá mi lóhùn,
17Nítorí pé òun yóò lọ̀ mí lúúlúú pẹ̀lú ìjì ńlá,
18Òun kì yóò jẹ́ kí èmi kí ó rí ẹ̀mí mi,
19Bí mo bá sọ ti agbára, wò ó!
20Bí mo tilẹ̀ dá ara mi láre, ẹnu ara mi yóò dá mi lẹ́bi;
21“Olóòótọ́ ni mo ṣe,
22Ohùn kan náà ni, nítorí náà ni èmi ṣe sọ:
23Bí ìjàǹbá bá pa ni lójijì,
24Nígbà tí a bá fi ayé lé ọwọ́ ènìyàn búburú;
25“Ǹjẹ́ nísinsin yìí ọjọ́ mi yára ju oníṣẹ́ lọ,
26Wọ́n kọjá lọ bí ọkọ̀ eèsún papirusi tí ń sáré lọ;
27Bí èmi bá wí pé, ‘Èmi ó gbàgbé arò ìbìnújẹ́ mi,
28Ẹ̀rù ìbànújẹ́ mi gbogbo bà mí,
29Bí ó bá ṣe pé ènìyàn búburú ni èmi,
30Bí mo tilẹ̀ fi ọṣẹ dídì wẹ ara mi,
31síbẹ̀ ìwọ ó gbé mi wọ inú ihò
32“Nítorí Òun kì í ṣe ènìyàn bí èmi,
33Bẹ́ẹ̀ ni kò sí alátúnṣe kan ní agbede-méjì wa
34Kí ẹnìkan sá à mú ọ̀pá Ọlọ́run kúrò lára mi,
35Nígbà náà ni èmi ìbá sọ̀rọ̀, èmi kì bá sì bẹ̀rù rẹ̀;