1Ohùn ti Olúwa wí nìyìí:
2Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli
3Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀,
4Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli,
5Nítorí pé Juda àti Israẹli ni
6“Sá kúrò ní Babeli!
7Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa;
8Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́.
9“ ‘À bá ti wo Babeli sàn,
10“ ‘Olúwa ti dá wa láre,
11“Ṣe ọfà rẹ ní mímú,
12Gbé àsíá sókè sí odi Babeli!
13Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀,
14Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀,
15“Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀,
16Nígbà tí ará omi ọ̀run hó
17“Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀,
18Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà,
19Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí;
20“Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi,
21Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀;
22pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin,
23Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn,
24“Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,”
25“Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun
26A kò ní mú òkúta kankan láti
27“Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà!
28Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀,
29Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún,
30Gbogbo àwọn jagunjagun
31Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn
32Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́
33Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí:
34“Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run,
35Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,”
36Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí:
37Babeli yóò parun pátápátá,
38Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù
39Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè,
40“Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn
41“Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé.
42Òkun yóò ru borí Babeli,
43Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro,
44Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli
45“Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀
46Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú
47Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan
48Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn,
49“Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli,
50Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró.
51“Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn:
52“Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí,
53Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run,
54“Ìró igbe láti Babeli,
55Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ,
56Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀,
57Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí,
58Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:
59Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
60Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
61Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
62Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
63Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
64Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’ ”