1“Ó jẹ́ pé nísinsin yìí bí ẹnìkan bá wà tí yóò dá wa lóhùn?
2Nítorí pé ìbínú pa aláìmòye,
3Èmi ti rí aláìmòye ti ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lulẹ̀,
4Àwọn ọmọ rẹ̀ kò jìnnà sí ewu,
5Ìkórè oko ẹni tí àwọn tí ebi ń pa sọ̀ di jíjẹ,
6Bí ìpọ́njú kò bá ti inú erùpẹ̀ jáde wá ni,
7Ṣùgbọ́n a bí ènìyàn sínú wàhálà,
8“Ṣùgbọ́n bí ó ṣe tèmi, ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ní èmi yóò ti ṣìpẹ̀,
9Ẹni tí ó ṣe ohun tí ó tóbi tí a kò lè ṣe àwárí,
10Tí ń rọ̀jò sí orí ilẹ̀ ayé
11Láti gbé àwọn orílẹ̀-èdè lékè
12Ó yí ìmọ̀ àwọn alárékérekè po,
13Ó mú àwọn ọlọ́gbọ́n nínú àrékérekè ara wọn,
14Wọ́n sáré wọ inú òkùnkùn ní ọ̀sán;
15Ṣùgbọ́n ó gba tálákà là ní ọwọ́ idà,
16Bẹ́ẹ̀ ni ìrètí wà fún tálákà,
17“Kíyèsi i, ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run bá wí,
18Nítorí pé òun a máa pa ni lára, síbẹ̀ òun a sì tún dì í ní ìdì ìtura,
19Yóò gbà ọ́ nínú ìpọ́njú mẹ́fà,
20Nínú ìyanu yóò gbà ọ́ lọ́wọ́ ikú
21A ó pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ iná ahọ́n,
22Ìwọ yóò rẹ́rìn-ín nínú ìparun àti ìyàn,
23Nítorí pé ìwọ ti bá òkúta igbó mulẹ̀,
24Ìwọ ó sì mọ̀ pé àlàáfíà ni ibùjókòó rẹ wà,
25Ìwọ ó sì mọ̀ pẹ̀lú pé irú-ọmọ rẹ ó sì pọ̀
26Ìwọ yóò wọ isà òkú rẹ ní ògbólógbòó ọjọ́,
27“Kíyèsi i, àwa ti wádìí rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní ó rí!