1Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé,
2“Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,
3Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò,
4Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa;
5“Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi;
6Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí,
7Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu,
8Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó
9Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn,
10“Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi,
11Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe,
12Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà;
13Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́,
14Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀
15gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀,
16“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye,
17Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí?
18O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘Ènìyàn búburú ní ìwọ,’
19mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé
20Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú,
21“Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn,
22Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú,
23Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan,
24Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí,
25nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn,
26Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn
27nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i,
28kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀,
29Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi?
30kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba
31“Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé,
32Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi
33Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà?
34“Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi,
35‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀,
36Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin,
37Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀;