1Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí Olúwa,
2Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́
3Nítorí Olúwa Ọlọ́run títóbi ni,
4Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà,
5Tirẹ̀ ni Òkun, nítorí òun ni ó dá a
6Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín,
7nítorí òun ni Ọlọ́run wa,
8“Ẹ má ṣe sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ní Meriba,
9nígbà tí àwọn baba yín dán mi wò
10Fún ogójì ọdún ni èmi fi bínú sí ìran náà;
11Nítorí náà ni mo kéde ìbúra nínú ìbínú mi,