1Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi;
2Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ;
3Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà;
4Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú;
5Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run;
6Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá,
7Olúwa jẹ ọba títí láé;
8Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo;
9Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,
10Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ,
11Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni;
12Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí;
13Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi!
14kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ
15Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́;
16A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀;
17Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú,
18Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé,
19Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí;
20Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa;