1Fi ìdájọ́ fún àwọn ọba, Ọlọ́run,
2Yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú òdodo,
3Àwọn òkè ńlá yóò máa mú àlàáfíà fún àwọn ènìyàn
4Yóò dáàbò bo àwọn tí a pọ́n lójú láàrín àwọn ènìyàn
5Àwọn òtòṣì àti aláìní
6Yóò dàbí òjò tí ó ń rọ̀ sórí pápá ìrẹ́mọ́lẹ̀,
7Àwọn olódodo yóò gbilẹ̀ ni ọjọ́ rẹ̀
8Yóò máa jẹ ọba láti òkun dé òkun
9Àwọn tí ó wà ní aginjù yóò tẹríba fún un
10Àwọn ọba Tarṣiṣi àti ti erékùṣù
11Gbogbo ọba yóò tẹríba fún un
12Nítorí yóò gba àwọn aláìní
13Yóò káàánú àwọn aláìlera àti aláìní
14Yóò ra ọkàn wọn padà lọ́wọ́ ẹ̀tàn àti ipá
15Yóò sì pẹ́ ní ayé!
16Kí ìkúnwọ́ ọkà wà lórí ilẹ̀;
17Kí orúkọ rẹ̀ kí ó wà títí láé;
18Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli,
19Olùbùkún ni orúkọ rẹ̀ tí ó lógo títí láé;
20Èyí ni ìparí àdúrà Dafidi ọmọ Jese.