1Gbà mí, Ọlọ́run,
2Mo ń rì nínú irà jíjìn,
3Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́;
4Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí
5Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run;
6Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi,
7Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn,
8Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi;
9nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run,
10Nígbà tí mo sọkún
11nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà,
12Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi,
13Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni
14Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀,
15Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀
16Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ;
17Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ:
18Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là;
19Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá;
20Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́,
21Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi,
22Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn
23Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran,
24Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn;
25Kí ibùjókòó wọn di ahoro;
26Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù,
27Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn;
28Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè
29Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí,
30Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga
31Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ
32Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀:
33Olúwa, gbọ́ ti aláìní,
34Kí ọ̀run àti ayé yìn ín,
35nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là
36àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀,