1Ẹ gbọ́ èyí, gbogbo ènìyàn!
2Àti ẹni tí ó ga àti ẹni tí ó kéré
3Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ọgbọ́n,
4èmi yóò dẹ etí mi sílẹ̀ sí òwe,
5Èéṣe ti èmi yóò bẹ̀rù nígbà tí ọjọ́ ibi dé?
6àwọn tí o gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ wọn,
7Kò sí ọkùnrin tí ó lè ra ẹ̀mí ẹnìkejì rẹ̀
8Nítorí ìràpadà fún ẹni jẹ́ iyebíye
9ní ti kí ó máa wà títí ayé
10Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rí ọkùnrin ọlọ́gbọ́n tí ó kú,
11Ibojì wọn ni yóò jẹ́ ilé wọn láéláé,
12Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí o wà nínú ọlá kò dúró pẹ́
13Èyí ni òtítọ́ àwọn ènìyàn tí ó
14Gẹ́gẹ́ bí àgùntàn ni a tẹ́ wọn sínú isà òkú
15Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ra ọkàn mi padà
16Má ṣe bẹ̀rù nígbà tí ẹnìkan bá di ọlọ́rọ̀.
17Nítorí kì yóò mú ohun kan lọ nígbà tí ó bá kú,
18Nígbà tí ó wà láyé, ó súre fún ọkàn ara rẹ̀.
19Òun yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ìran àwọn baba rẹ̀
20Ọkùnrin tí ó ní ọlá tí kò ní òye dàbí ẹranko tí ó ṣègbé.