1Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀?
2Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn:
3Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni Ìwọ;
4Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ;
5Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà;
6Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn;
7Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà;
8“Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa;
9Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú;
10Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá,
11Má ṣe jìnnà sí mi,
12Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká;
13Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri,
14A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi,
15Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì,
16Àwọn ajá yí mi ká;
17Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi;
18Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn
19Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi.
20Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà,
21Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún;
22Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi;
23Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín!
24Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra
25Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá;
26tálákà yóò jẹ yóò sì yó;
27Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí
28nítorí ìjọba ni ti Olúwa.
29Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn;
30Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín;
31Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀