1Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún,
2nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn
3Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri;
4Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi,
5Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi
6Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ
7Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́
8Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú;
9Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba
10Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri
11Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní
12Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un
13Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò
14Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí
15Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa
16Nítorí kò rántí láti ṣàánú,
17Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀:
18Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù
19Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara,
20Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá;
21Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè,
22Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí,
23Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́,
24Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà
25Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi;
26Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi;
27Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí
28Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre,
29Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú
30Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi
31Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní