1Ọlọ́gbọ́n obìnrin kọ́ ilé e rẹ̀,
2Ẹni tí ń rìn déédé bẹ̀rù Olúwa,
3Ọ̀rọ̀ aṣiwèrè a máa ṣokùnfà pàṣán fún ẹ̀yìn rẹ̀,
4Níbi tí kò sí ẹran, ibùjẹ ẹran a máa mọ́ tónítóní,
5Ẹlẹ́rìí tí ń ṣọ òtítọ́ kì í tan ni
6Ẹlẹ́gàn ń wá ọgbọ́n kò sì rí rárá,
7Má ṣe súnmọ́ aláìgbọ́n ènìyàn,
8Ọgbọ́n olóye ni láti ronú jinlẹ̀ nípa ọ̀nà wọn
9Aláìgbọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ nígbà tí ó yẹ kí ó ṣe àtúnṣe ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀
10Ọkàn kọ̀ọ̀kan ló mọ ẹ̀dùn ọkàn tirẹ̀
11A ó pa ilé ènìyàn búburú run,
12Ọ̀nà kan wà tí ó dàbí i pé ó dára lójú ènìyàn,
13Kódà nígbà tí a ń rẹ́rìn-ín, ọkàn le è máa kérora;
14A ó san án lẹ́kùnrẹ́rẹ́ fún aláìgbàgbọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀,
15Òpè ènìyàn gba ohun gbogbo gbọ́
16Ọlọ́gbọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run ó sì kórìíra ibi
17Ẹni tí ó máa ń tètè bínú máa ń hùwà aṣiwèrè,
18Òpè jogún ìwà òmùgọ̀
19Ènìyàn ìkà yóò tẹríba níwájú àwọn ènìyàn rere
20Kódà àwọn aládùúgbò tálákà kò fẹ́ràn rẹ̀,
21Ẹni tí ó kẹ́gàn aládùúgbò o rẹ̀ ti dẹ́ṣẹ̀
22Ǹjẹ́ àwọn tí ń pète ibi kì í ṣìnà bí?
23Gbogbo iṣẹ́ àṣekára ló máa ń mú èrè wá,
24Ọrọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn ni adé orí wọn
25Ẹlẹ́rìí tí ó ṣọ òtítọ́ gba ẹ̀mí là
26Nínú ìbẹ̀rù Olúwa ni ìgbẹ́kẹ̀lé tí ó lágbára,
27Ìbẹ̀rù Olúwa jẹ́ orísun ìyè,
28Ènìyàn púpọ̀ ní ìlú jẹ́ ògo ọba,
29Onísùúrù ènìyàn ní òye tí ó pọ̀,
30Ọkàn tí ó lálàáfíà fi ìyè mú kí ọjọ́ ayé gùn fún ara,
31Ẹni tí ó fi ìyà jẹ aláìní ń fi ìkórìíra hàn
32Nígbà tí ìyọnu bá dé, a fa àwọn búburú lulẹ̀,
33Ọgbọ́n wà nínú ọkàn olóye
34Òdodo a máa gbé orílẹ̀-èdè lékè,
35Ọba a máa ní inú dídùn sí ìránṣẹ́ tí ó gbọ́n