1Ìgbà náà ni Jobu sì dáhùn wí pé,
2“Àní lónìí ni ọ̀ràn mi korò;
3Háà! èmi ìbá mọ ibi tí èmí ìbá wá
4Èmi ìbá sì to ọ̀ràn náà níwájú rẹ̀,
5Èmi ìbá sì mọ ọ̀rọ̀ tí òun ìbá fi dá mi lóhùn;
6Yóò ha fi agbára ńlá bá mi wíjọ́ bí?
7Níbẹ̀ ni olódodo le è bá a wíjọ́,
8“Sì wò ó, bí èmi bá lọ sí iwájú,
9Ni apá òsì bí ó bá ṣiṣẹ́ níbẹ̀, èmi kò rí i,
10Ṣùgbọ́n òun mọ ọ̀nà tí èmi ń tọ̀,
11Ẹsẹ̀ mí ti tẹ̀lé ipasẹ̀ ìrìn rẹ̀;
12Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò padà sẹ́yìn kúrò nínú òfin ẹnu rẹ̀,
13“Ṣùgbọ́n onínú kan ni òun, ta ni yóò sì yí i padà?
14Nítòótọ́ ohun tí a ti yàn fún mi ní í ṣe;
15Nítorí náà ni ara kò ṣe rọ̀ mí níwájú rẹ̀;
16Nítorí pé Ọlọ́run ti pá mi ní àyà,
17Nítorí tí a kò tí ì ké mi kúrò níwájú òkùnkùn,